Ibà jẹ ikan ninú àwọn àrùn tó pa àwọn èniyàn jù ni àwọn orilẹ̀-èdè Ìwọ̀-oòrùn ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú. Yorùbá ti ńlo ewé àti egbò igi ti ó wà ni oko àti àyiká ilé lati ṣe àgbo fún itọ́jú ibà ki Òyinbó tó gba ilú tó sọ ewé àti egbò igi di hóró oògùn ibà.
English Translation: malaria is one of the biggest killers of people all over Africa. Yoruba people have been using herbs and tree barks that are found all over Yoruba land to make herbal concoctions or herbal remedies to care for malaria long before Europeans arrived in Africa and turned the leaves and barks into malaria medicines.
Originally posted 2020-09-08 02:39:18. Republished by Blog Post Promoter
Ninú Ẹ̀yà mẹrin-din-logoji orilẹ̀ èdè Nigeria, ẹ̀yà mẹ́fà ni o wa ni ipinlẹ Yorùbá lápapọ̀. Àwọn ẹ̀yà wọnyi ni: Èkó – ti olú ilú rẹ jẹ Ìkẹjà; Èkiti – ti olú ilú rẹ jẹ Adó-Èkiti; Ò̀gùn – ti olú ilú rẹ jẹ Abẹ́òkúta; Ondo – ti olú ilú rẹ jẹ Àkúrẹ́; Ọ̀ṣun – ti olú ilú rẹ jẹ Òṣogbo àti Ọyọ – ti olú ilú rẹ jẹ Ìbàdàn.
ọ̀pọ̀ ara Ọ̀ṣun dibò àti bójú tó ibò wọn – Osun voters voted and protected their votes
Ni Òkè-Òkun, bi enia ba ni ẹjọ́ ni ilé-ẹjọ́, tàbi ó ti ṣe ẹ̀wọ̀n ri, tàbi hùwà àbùkù miran, irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò lè gbé àpóti ibò ṣùgbọ́n, ti kò bá ni itiju, ti ó gbé àpóti ibò, ọ̀pọ̀ àwọn èrò ilú kò ni dibò fún irú ẹni bẹ́ẹ̀. Eyi kò ri béè ni orilẹ-èdè Nigeria, nitori, ẹlẹ́wòn, eleru, olè, apànìyàn àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ, ti ó di olówó ojiji ló ńgbé àpóti ibò nitori wọn mọ̀ pé àwọn lè fi èrú dé ipò.
Àwọn èrò ẹ̀yà Ọ̀ṣun fi òwe Yorùbá ti o ni “Ọ̀pọ̀ ni eṣú fi ńya igi oko” hàn ni idibò ti ó kọjá ni ọjọ́ Àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹsan, oṣù kẹjọ, ọdún Ẹgbẹlemẹrinla, wọn kò bẹ̀rù bi Ìjọba àpapọ̀ Nigeria ti kó Ológun àti ohun ijà ti àwọn ará ilú lati da ẹ̀rù bà wọn. Wọn tú jáde lati fi ọ̀pọ̀ dibò àti bójú tó ibò wọn lati gbé Góminà Ọ̀gbẹ́ni Rauf Arẹ́gbẹ́ṣọlá padà.
ENGLISH TRANSLATION
Out of the thirty-six States in Nigeria, six are in Yoruba land altogether. These States are: Lagos – State capital Ikeja; Ekiti – State capital at Ado-Ekiti; Ogun – State capital at Abeokuta; Ondo – State capital at Akure; Osun – State capital at Osogbo and Oyo with the State capital at Ibadan.
In the developed world/abroad, if a person has a pending law suit in the Court, or has once been in prison, or has behaved in a disgraceful manner, such person cannot vie for a Political position, but even if such a person has no sense of shame, and decided to vie, many of the masses would not vote for such. This is not the case in Nigeria, because a prisoner, fraudster, thief, killers/assassin etc with their ill-gotten wealth/money could vie for political position since they know they could win through fraudulent means.
The people of Osun State reflected the application of the Yoruba proverb that said “It is by means of their numbers that Locusts could tear down a tree” during the Governorship Election held on Saturday, ninth August, 2014, when they defied the Federal might as Soldiers and armoured tanks were drafted to intimidate the people. They trooped out in their numbers to vote and protect their votes to re-elect Governor (Mr) Rauf Aregbesola.
Originally posted 2014-08-15 22:49:34. Republished by Blog Post Promoter
Ìtàn yi dá lori Bàbá ti aládũgbò mọ si “Bàbá Beyioṣe”. Bàbá yi jẹ onígbàgbọ́, ti ki ja tabi ṣe ãpọn. O bi ọmọ mẹta ti wọn jọ ngbe nitori iyawo rẹ ti kú. Ni ilé ti o ngbe, ó fi ifẹ hàn si àwọn olùbágbé àti aládũgbò. Bi Bàbá yi bá fẹ́ la ija yio sọ pé “ẹ má jà, a ò mọ ohun ti Ọlọrun fi ohun ti ẹ ńjà lé lori ṣe, nitori na ‘bi eyi o ṣe, omiran yio ṣe’.
Ni ọjọ́ kan, ọmọ kú fún obinrin olùbágbélé Bàbá Beyioṣe. Bàbá tún dé ọdọ obinrin yi lati tu ninu, o sọ fún pe “Bi eyi o ṣe, omiran yio ṣe – ẹ pẹ̀lẹ́, a o mọ̀ ohun ti Ọlọrun fi ṣe”. Ọrọ ìtùnú yi bi ẹniti o ṣe ọ̀fọ̀ ọmọ ti ó kú ninu tó bẹ gẹ ti o fi gbèrò pe ohun yio dán ìgbàgbọ́ Bàbá Beyioṣe wo nipa wiwo ohun ti yio ṣe ti ọmọ ti rẹ nã bá kú.
Ogi – Corn starch. Courtesy: @theyorubablog
Ogi – Corn pap. Courtesy: @theyorubablog
Ni òwúrọ̀ ọjọ́ kan, Bàbá Beyioṣe, sọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé ohun fẹ ji dé ibikan. Ó ṣe ètò pé ki wọn mu ògì àti àkàrà ni òwúrọ̀ ọjọ́ na. Àwọn ọmọ ji, wọn lọ si àrò, wọn po ògì lai mọ pe, obinrin ti ọmọ rẹ ku ti bu májèlé si ògì yi. Àwọn ọmọ gbé ògì wọlé ṣùgbọ́n wọn dúró de ikan ninu wọn ti ó lọ ra àkàrà. Nigbati ẹni ti ó lọ ra àkàrà de, ẹ̀gbọ́n àgbà pin àkàrà ṣùgbọ́n ija bẹ silẹ nitori ẹni ti o pin akara ko pin daradara. Nibi ti wọn ti ńja, ògì ti o jẹ ounjẹ àárọ̀ àwọn ọmọ Bàbá Beyioṣe dànù. Ori igbe ògì ti ó dànù ni àwọn ọmọ wa nigbati Bàbá Beyioṣe wọlé. Gẹ́gẹ́ bi iṣe rẹ, ó sọ fún àwọn ọmọ pé “ẹ má jà, bi eyi o ṣe, omiran yio ṣe – a o mọ ohun ti Ọlọrun fi ṣe”.
Obinrin ti o fi májèlé si ògì, ti o reti ki àwọn ọmọ Bàbá Beyioṣe ó kú, ba jade nigbati ó gbọ́ ohun ti o sọ lati tu àwọn ọmọ rẹ ninu. Ó jẹ́wọ́ pe nitotọ, onígbàgbọ́ ni Bàbá Beyioṣe nitori ohun ti ohun ṣe, ó wá tọrọ idariji. Bàbá Beyioṣe dariji, ó fún àwọn ọmọ lówó lati ra ounjẹ miran.
Gẹ́gẹ́bí ọ̀rọ̀ Yorùbá ti ó ni “Iṣẹ́ ni oogun ìṣẹ́”, jẹ́ òtítọ́, bi òṣìṣẹ́ bá ri owó gbà ni àsìkò, tàbi gba ojú owó fún iṣẹ́ ti wọn ṣe. Òṣìṣẹ́ ti ó ṣiṣẹ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ wákàtí/àkókò lórí owó kékeré, kò lè bọ́ ninu ìṣẹ́, nitori, ọlọ́rọ̀ kò ni ìtìjú lati jẹ òógùn Òṣìṣẹ́. Ọ̀pọ̀ òṣìṣẹ́, a fi ìtìjú gé ara wọn kúrú nipa àti bèrè ẹ̀tọ́ wọn. Òṣìṣẹ́ míràn a ṣe iṣẹ́ ọ̀fẹ́ fún ọlọ́rọ̀ tàbi ki wọn fúnra wọn gé owó ise wọn kúru lati ri ojú rere ọlọ́rọ̀, nipa èyi, wọn á pa owó fún ọlọ́rọ̀ ni ìparí ọdún.
Ọ̀rọ̀ Yorùbá ti o ni “Ọ̀dájú ló bi owó, ìtìjú ló bi igbèsè” ṣe ló lati ba oloro tàbi o ni ilé-iṣẹ́ ti á lo gbobo ọ̀nà lati ma gba “Ẹgbẹ́-òṣìṣẹ́” láyè. Ọlọ́rọ̀ kò ni ìtìjú lati lo òṣìṣẹ́ fún owó kékeré. A lè lo ọ̀rọ̀ yi lati gba Òṣìṣẹ́ ni ìyànjú ki wọn má tara wọn ni ọ̀pọ̀, nipa bi bèrè owó ti ó yẹ fún iṣẹ́ ti wọn ṣe àti pé ki òṣìṣẹ́ gbìyànju lati kọ iṣẹ́ mọ́ iṣẹ́ lati wà ni ipò àti bèrè ojú owó.
(Olóògbé Ọ̀jọ̀gbọ́n Olikoye Ransome Kuti – Oníṣègùn-Ọmọdé ti gbogbo àgbáyé mọ̀, Òjíṣẹ́-Òṣèlú Nigeria ni ọdún keji-din-lọ́gbọ̀n si ọdún keji-lé-lógún sẹhin, ṣe irànlọ́wọ́ gidigidi nipa di-din “Ikú ọmọdé kù” nipa ẹ̀kọ́-ìlàjú fún gbogbo ilú àti abúlé. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ ni, ìlàjú lóri ẹ̀rọ amóhùn-máwòrán àti ẹ̀rọ asọ̀rọ̀-mágbèsi gbàlà lọ́wọ́ ikú igbẹ́-gburu, nipa ìmọ̀ “Omi Oni-yọ lati dipò omi ara”.
Ẹ ṣe àyẹ̀wò àpẹrẹ bi Àbíkú ti din-ku ni orilẹ̀ èdè Nigeria, nitori eyi orúkọ Àbíkú din-kù:
Ikú ọmọ ti kò ti pé ọdún marun ni ọdún mẹrin-lé-lógún sẹhin jẹ́ Igba-lé-mẹ́tàlá
Ikú ọmọ ti kò ti pé ọdún marun ni ọdún keji sẹhin ti din-kù si Mẹrin-lé-lọgọfa.
ENGLISH TRANSLATION
An Internationally acclaimed Paediatrician, Late Professor Olikoye Ransome-Kuti – Nigeria’s Minister of Health 1986 to 1992 contributed greatly to the reduction of Child Mortality in Nigeria through his Television/Radio Enlightenment Programme as well as promotion of Rural Health Education. Many children were saved from death through diarrhoea through his Television and Radio Enlightenment Programme on “Oral Dehydration Therapy – ORT”.
Check out example of how Child Mortality has reduced in Nigeria, hence names associated with Child Mortality has reduced. According to UNICEF statistics:
Under 5 Mortality Rate (U5MR) 1990 – 213
Under 5 Mortality Rate (U5MR) 2012 – 124
Orúkọ Yorùbá fú́n Àbíkú – Yoruba Name associated with child-mortality
Igé Kúrú Orúkọ Àbíkú – Short form of Name associated with child-mortality
Itumọ – Meaning in English
Gbókọ̀yi
Kọyi
The forest rejected this
Kòkúmọ́
Kòkú
Not dying again
Malọmọ
Malọ
Do not go again
Igbẹkọyi
Kọyi
The dungeon rejected this
Akisatan
No more rags (worn out clothes or rags were used as diapers)
Kòsọ́kọ́
No hoe (e.g. hoe is synonymous with any instrument used in digging the grave i.e. Digger, Shovel, etc
Ọkọ́ya
The hoe is broken (i.e. hoe is synonymous with any digging instruments)
Ẹkúndayọ̀
Dayọ̀
Weeping has turned to joy
Rẹ̀milẹ́kún
Rẹmi
Pacify me from weeping
Ògúnrẹ̀milẹ́kún
Rẹ̀milẹ́kún
The god of iron (Ogun) has pacified me from weeping
Olúwarẹ̀milẹ́kún
Rẹ̀mi/Rẹ̀milẹ́kún
God has pacified me from weeping
Bámitálẹ́
Tálẹ́
Remain with me till the evening/end
Fadaisi/Fadayisi
Daisi/Dayisi
“Ifa” has spared this
Ogundaisi/Ogundayisi
Daisi/Dayisi
“Ogun” has spared this
Mátànmijẹ
Mátànmi
Don’t deceive me
Jokotimi
Joko
Seat with me
Dúrójayé
Dúró/Jayé
Stay to enjoy the world
Dúró́sinmi
Dúró/Sinmi
Stay to bury me (Me here means the plea from the child’s parent)
Dúróorikẹ
Rikẹ
Stay to bury me (Me here means the plea from the child’s parent)
Dúrótimi
Rotimi
Stay with me
Bámidúró
Dúró
Stand with me
Jokotọla
Joko/Tọla
Seat with wealth
Adérọ́pò
Rọ́pò
He/she who came to replace
Olúwafirọ́pò
Rọ́pò/Firọ́pò
God’s replacement
Dúródọlá
Dúró/Dọlá
Wait for wealth
Kilanko
Lanko
What are we naming
Ajá
Dog
Ẹnilọlóbọ̀
Ẹnilọ
He/she who left has returned
Dúrójogún
Dúró/Jogún
Live/Stay to inherit.
Originally posted 2014-09-23 09:01:44. Republished by Blog Post Promoter
Yorùbá ní “Ã ò pé kámá jọ Baba ẹni timútimú, ìwà lọmọ àlè”. Òwe yi bá ọpọlọpọ Yorùbá tí o nyi orúkọ ìdílé wọn padà nítorí ẹ̀sìn lai yi ìwà padà̀ lati bá orúkọ titun áti ẹ̀sìn mu. Yorùbá ni “ilé lanwo ki a tó sọmọ lórúkọ” nítorí èyí, ọpọlọpọ orúkọ ìdílé ma nbere pẹ̀lú orúkọ òrìṣà ìdílé bi: Ògún, Ṣàngó, Ọya, Èṣù, Ọ̀sun, Ifá, Oṣó àti bẹ̃bẹ lọ. Fún àpẹrẹ: Ògúnlànà, Fálànà, Ṣólànà ti yi padà sí Olúlànà. Ìgbà míràn ti wọn bá lò lára orúkọ àwọn òrìṣa yi wọn a ṣe àyípadà si, fún àpẹrẹ: “Eṣubiyi” di “Èṣúpòfo”.
“Esupofo”? Njẹ Èṣù pòfo bí, nígbàtí ẹni ti o yi orúkọ padà sí “Èṣúpòfo” njale. . .
Njẹ Èṣù pòfo bí, nígbàtí ẹni ti o yi orúkọ padà sí “Èṣúpòfo” njale, ṣiṣẹ́ gbọ́mọgbọ́mọ, purọ́, kówó ìlú jẹ, àti bẹ̃bẹ lọ? Ótì o, Èṣù o pòfo, ìwà lọmọ àlè. Ọmọ àlè ti pọ si nítorí ìwà Èṣu ti pọ si ni ilẹ̀ Yorùbá. Kò sí nkan tí óburú ninú orúkọ yíyí padà, èyí ti o burú ni kí a yí orúkọ padà lai yi ìwà padà. Ẹ fi ìwà rere dípò ìporúkodà.
ENGLISH TRANSLATION
The Yoruba people have a saying that “It is not enough to have a striking resemblance to one’s father, character distinguishes a bastard”. This proverb refers to Yoruba people that replace their family names without matching change of character to go with the name or religion. Another Yoruba saying goes that: “home is observed before naming a child” as a result of this, and so family names are derived with a prefix of the name of the gods and goddesses worshiped in the family such as Ò̀̀̀̀̀̀gun – god of iron/war, Ṣango – god of thunder, Oya – Sango’s wife, Eṣu – Satan, Osun – river goddess, Ifa – Divination, Oso – Wizard etc. For example names like: Ogunlana, Falana, Solana have mostly been changed to “Olulana”. Sometimes, when part of these gods/goddess names are used it is often changed, for example: “Esubiyi – delivered by Satan” is turned “Esupofo – satan has lost”. Continue reading →
Originally posted 2015-01-23 10:15:54. Republished by Blog Post Promoter
Ọjọ́ keje, oṣù kọkanla ọdún Ẹgbàá, ìròyìn kàn pé Joe Biden àti Igbakeji rẹ Kamala Harris ni wọ́n yàn si ipò Àrẹ kẹrindinlaadọta ti yio gun ori oyè lati Ogún ọjọ́, oṣù kini ọdún Ẹgbàálékan.
Obinrin àkọ́kọ́ Igbakeji Àrẹ Kamala Harris di ẹni ìtàn – inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ará ilú dún lati gbọ́ iroyin ayọ̀ yi. Èrò tu jade lati yọ̀.
Obinrin ti jẹ Àrẹ ni àwọn orilẹ̀-èdè míràn tàbi jẹ ọba ni ilú Òyinbó ṣùgbọ́n àkọ́kọ́ rè é ni orilẹ̀-èdè America ti obinrin di Igbakeji Àrẹ pàtàki ti ó tún jẹ aláwọ̀dúdú. Ni orile-ede Nigeria, ọkùnrin ló pọ̀ ni ipò Òṣèlú, kò ti si obinrin ti o di Gómìnà ki a má ti sọ ipò Àrẹ.
Yorùbá ni “Gbogbo lọ ọmọ”, èyi fihàn pé Yorùbá ka obinrin àti ọkùnrin si ọmọ, ṣùgbọ́n bi ìyàwó bá wà ti kò bi ọkùnrin, inú wọn ki i dùn pàtàki àwọn ti kò kàwé. Èyi yẹ kó kọ́ àwọn obinrin ti ó ḿbímọ rẹpẹtẹ nitori wọn fẹ́ bi ọkùnrin pé “Gbogbo lọ ọmọ”, èyi ti ó ṣe pàtàki ni ki Ọlọrun fún ni lọ́mọ rere.
ENGLISH LANGUAGE
The news of election of Joe Biden and Kamala Harris as the 46th President/Vice President of America broke out on November Seven (07), 2020 and would be sworn in on January 20, 2021.
Yorùbá ka ọmọ bibi si ohun pàtàki fún ìdílé, nitori èyi, tijó tayọ̀ ni Yorùbá ma fi nki ọmọ titun káàbọ̀ si ayé. Gẹ́gẹ́bí Ọ̀gá ninu Olórin ilẹ̀-aláwọ̀ dúdú, Olóyè Ebenezer Obey ti kọ́ “Ẹ̀bùn pàtàki ni ọmọ bibi…”. Ìlú ti igbe ọmọ titun kò bá dún, ìlú naa ́a kan gógó. Eleyi lo ṣẹlẹ̀ ni ìlú Olúróhunbí.
Fún ìgbà pípẹ́, àwọn obinrin ìlú kò ri ọmọ bi, nitorina, gbogbo wọn lọ si ọ̀dọ̀ Òrìṣà Ìrókò lati lọ tọrọ ọmọ. Oníkálukú wọn jẹjẹ oriṣiriṣi ohun ti wọn ma fún Ìrókò ti wọ́n bá lè ri ọmọ bi. Ẹlòmiràn jẹ ẹ̀jẹ́ Ewúrẹ́, òmíràn Àgùntàn tàbi ohun ọ̀gbìn. Yorùbá ni “Ẹyin lohùn, bi ó bá balẹ̀ ko ṣẽ ko”, kàkà ki Olurohunbi, ìyàwó Gbẹ́nàgbẹ́nà, jẹ ẹ̀jẹ́ ohun ọ̀sìn tàbi ohun àtọwọ́dá, o jẹ ẹ̀jẹ́ lọ́dọ̀ Ìrókò pé ti ohun bá lè bi ọmọ, ohun yio fún Ìrókò lọ́mọ naa.
Ewúrẹ́ – Goat Courtesy: @theyorubablog
Àgùntàn – Sheep Courtesy: @theyorubablog
iṣu – Yam Courtesy: @theyorubablog
Lai pẹ́, àwọn obinrin ìlú bẹ̀rẹ̀ si bimọ. Oníkálukú pada si ọ̀dọ̀ Ìrókò lati lọ san ẹ̀jẹ́ wọn, ṣùgbọ́n Olúróhunbí kò jẹ́ mú ọmọ rẹ̀ silẹ lati san ẹ̀jẹ́ ti ó jẹ́.
Òwe Yorùbá ni “Bi ojú bá sé ojú, ki ohun má yẹ̀ ohun”, ṣùgbọ́n
Ọmọ titun – a baby Courtesy: @theyorubablog
Olúróhunbí ti gbàgbé ẹ̀jẹ́ ti ó jẹ́.
Ni ọjọ́ kan, Olúróhunbí dágbére fún ọkọ rẹ̀ pé ohun fẹ́ lọ si oko ẹgàn/igbó, ó bá gba abẹ́ igi Ìrókò kọjá. Bi ó ti dé abẹ́ igi Ìrókò, Ìrókò gbamú, ó bá sọ di ẹyẹ. Ẹyẹ Olúróhunbí bẹ̀rẹ̀ si kọ orin lóri igi Ìrókò bayi:
Oníkálukú jẹ̀jẹ́ Ewúrẹ́, Ewúrẹ́
Ònìkàlùkú jẹjẹ Àgùntàn, Àgùntàn bọ̀lọ̀jọ̀
Olúróhunbí jẹ̀jẹ́ ọmọ rẹ̀, ọmọ rẹ̀ a pọ́n bí epo,
Olúróhunbí o, jain jain, Ìrókó jaini (2ce)
Nigbati, ọkọ Olúróhunbí reti iyàwó rẹ titi, ó bá pe ẹbi àti ará lati wa. Wọn wa Olúróhunbí titi, wọn kò ri, ṣùgbọ́n nigbati ọkọ rẹ̀ kọjá lábẹ́ igi Ìrókò to gbọ́ orin ti ẹyẹ yi kọ, ó mọ̀ pe ìyàwó ohun ló ti di ẹyẹ.
Gẹgẹbi iṣẹ́ rẹ (Gbénàgbénà), ó gbẹ́ èrè bi ọmọ, ó múrá fún, ó gbe lọ si abẹ́ igi Ìrókò. Òrìṣà inú igi Ìrókò, ri ère ọmọ yi, o gbã, ó sọ Olúróhunbí padà si ènìà.
Igi Ìrókò – Iroko Tree Courtesy: @theyorubabolg.com
Ọmọ langidi – Baby Doll Courtesy: @theyorubablog
Ìtàn yi kọ́ wa pé: igbèsè ni ẹ̀jẹ́, ti a bá dá ẹ̀jẹ́, ki á gbìyànjú lati san; ki a má da ẹ̀jẹ́ ti a kò lè san àti ki á jẹ́ ki ọ̀rọ̀ wa jẹ ọ̀rọ̀ wa. Continue reading →
Originally posted 2015-03-27 09:20:46. Republished by Blog Post Promoter
This website uses cookies to improve your experience. We'll assume you're ok with this, but you can opt-out if you wish. Cookie settingsACCEPT
Privacy & Cookies Policy
Privacy Overview
This website uses cookies to improve your experience while you navigate through the website. Out of these cookies, the cookies that are categorized as necessary are stored on your browser as they are essential for the working of basic functionalities of the website. We also use third-party cookies that help us analyze and understand how you use this website. These cookies will be stored in your browser only with your consent. You also have the option to opt-out of these cookies. But opting out of some of these cookies may have an effect on your browsing experience.
Necessary cookies are absolutely essential for the website to function properly. This category only includes cookies that ensures basic functionalities and security features of the website. These cookies do not store any personal information.
Any cookies that may not be particularly necessary for the website to function and is used specifically to collect user personal data via analytics, ads, other embedded contents are termed as non-necessary cookies. It is mandatory to procure user consent prior to running these cookies on your website.